2021
Jésù Krístì Ní Kí A Má a Jẹ Oúnjẹ Olúwa
Oṣù Kẹ́ta 2021


”Jésù Krístì Ní Kí Á Má a Jẹ Oúnjẹ Olúwa”, Làìhónà, Oṣù Kẹta 2021

Ọ̀rọ̀ Oṣooṣù Làìhónà Oṣù Kẹta 2021

Jésù Krístì Ní Kí Á Má a Jẹ Oúnjẹ Olúwa

À ńní ìwòsàn àti ìwẹ̀númọ́ bí a ṣe ńrántí Olùgbàlà wa ní ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀.

Àwòrán
Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn

Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn, láti ọwọ́ Carl Heinrich Bloch

Ṣíwájú ikú Rẹ̀, Jésù Krístì jẹ oúnjẹ kan tó kẹ́hìn tí à pè ní Oúnjẹ alẹ́ Olúwa. Ní òpín oúnjẹ náà, Ó fi oúnjẹ Olúwa hàn sí áwọn àtẹ̀lẹ́ Rẹ̀. Ó ja búrẹ́dì ó sì súre sí i. “Ṣe èyí ní ìrántí mi,” ni O wí (Luku 22:19). Lẹ́hin rẹ̀ Ó súre sí i, ó sì pín ife wáìnì fún wọn.

Àwòrán
ẹbí ńgba oúnjẹ Olúwa

Ara àwọn Ìjọsìn Ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀

Nígbà tí wọ́n ṣe ìmúpadàbọ̀sípò Ìjọ Jésù Krístì sí ayé, oúnjẹ Olúwa di ara ìjọ́sìn ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀. Ní ákokò ìjọsìn, àwọn tí ó di oyèàlúfà mú yíò bùkún oúnjẹ Olúwa, wọn yíò sì ṣe àbápín rẹ̀. Wọ́n gbàdúrà pẹ̀lú lílo àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé-mímọ́ (wo Moroni 4; 5). Lẹ́hìn èyí ni ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú ìjọ yíó jẹ búrẹ́dí tí wọn yíò sì mu omi láti rántí Jésù Krístì àti ìrúbọ Rẹ̀ fún wa, gẹ́gẹ́ bí Ó ti wí fún wa láti ṣe.

Àwòrán
ọmọdébìnrin ńgbàdúrà

Àwòrán nípasẹ̀ Angela Suitter

Múrasílẹ̀ láti ṣe Àbápín

Láti gbáradì fún oúnjẹ alẹ́ Olúwa, a gbọ́dọ̀ ronú nípa àwọn ìgbé ayé wa àti àṣàyàn wa lódodo. A gbọ́dọ̀ ronúpìwàdà kúrò nínú àwọn àṣìṣe àti ẹ̀ṣẹ̀ wa ti ọ̀sẹ̀ tó kọjá, pẹ̀lú bíbèèrè ìdáríjì lọ́wọ́ Ọlọ́run. A kò níláti jẹ́ pípé kí a tó jẹ oúnjẹ Olúwa, sùgbọ́n a gbọ́dọ̀ ní ìrẹ̀lẹ̀ ọkàn.

Àwòrán
Àdúrà ní Gẹ́tsémánì

Àdúrà ní Gẹ́tsémánì, láti ọwọ́ Del Parson

Jú Búrẹ́dì àti Omi lọ

Jíjẹ oúnjẹ Olúwa jẹ́ àkókò ọ̀wọ̀, mímọ́ kan. Àwọn àdúrà oúnjẹ Olúwa rán wa létí pé bí a ṣe ńjẹ́ búrẹ́dì, tí à ńmú omi, à ńrántí ara àti ẹ̀jẹ̀ tí Jésù Krístì fi fún wa. A ṣèlérí láti tẹ̀lé E kí á sì gbé ìgbé-ayé krìstẹ́nì. A ṣèlérí láti gbìyànjú láti pa àwọn òfin Ọlọ́run mọ́. Ní àbábọ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ yíó ma tùwá nínú, tọ́wa sọ́nà, àti wò wá sàn.

Àwòrán
ìrìbọmi

Àtúnṣe àwọn Májẹ̀mú

Nígbà tí àwa tí a ti ṣe ìrìbọmi bá jẹ oúnjẹ Olúwa pẹ̀lú ọkàn mímọ́, à ńtú àwọn májẹ̀mú tí a dá ní àkókò ìrìbọmi ṣe. Nínú èyí ní gbígba Ẹ̀mí Mímọ́ àti jíjẹ́ ìwẹ̀númọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ bí ẹni wípé a ṣẹ̀ṣẹ̀ tún ìrìbọmi ṣe lẹ́ẹ̀kansi. Èyí ni ìrètí àti àánú tí Jésù fún ẹnìkọ̀ọ̀kan wa. Kò tí ì pẹ́jù rárá láti ronúpìwàdà kí á sì gba ìdáríjì.

Àwòrán
Jésù Krístì fi oúnjẹ Olúwa lẹ́lẹ̀ fún áwọn Ará Néfì

Kí Ẹ Má a Rántí Mi Nígbàgbogbo, láti ọwọ́ Gary L.Kapp, a kò lè ṣe ẹ̀dà rẹ̀

Kínni Àwọn Ìwé Mímọ́ Sọ nipa Oúnjẹ Olúwa?

Kí á se àyẹ̀wò ara wa níti ẹ̀mí, kí a wo ara wa dénú pẹ̀lú òdodo, kí á tó jẹ oúnjẹ Olúwa (wo 1 Corinthians 11:28).

Lẹ́hìn tí Ó jíǹde, Jésù fi àwọn ènìyàn Rẹ̀ hàn ní àwọn Amẹ́ríkà bí wọn ó ti máa jẹ́ oúnjẹ Olúwa (wo 3 Néfì 18).

Àwọn wòlíì òde-òní sọ fún wa wípé kí á lo búrẹ́dì àti omi fún oúnjẹ Olúwa, ṣùgbọ́n ohun tí à ńjẹ tàbí mu kò fi bẹ́ẹ̀ jẹ́ nkan (wo Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 27:2). Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbá àwọn tó ní ẹ̀hún ara nílò láti lo ohun míràn tó dàbí búrẹ́dì.

Oúnjẹ Alẹ́ Ikẹ́hìn, láti ọwọ́ Carl Heinrich Bloch; àwòrán ọmọdébìnrin tó ńgbàdúrà láti ọwọ́ Angela Suitter; Àdúrà ní Gẹ́tṣémánì, láti ọwọ́ Del Parson; Kí Ẹ Má a Ráńtí Mi Nígbàgbogbo, láti ọwọ́ Gary L. Kapp, a kò lè ṣe ẹ̀dà rẹ̀

Tẹ̀