Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò
Hòsánnà sí Ọlọ́run Gíga Jùlọ
Ìpàdé Àpapọ̀ Gbogbogbò Oṣù Kẹrin 2023


Hòsánnà sí Ọlọ́run Gíga Jùlọ

Jésù Krístì fi ìṣẹ́gun wọ Jerusalem àti pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ti ọ̀sẹ̀ náà tí ó tẹ̀lé jẹ́ àpẹrẹ ẹ̀kọ́ tí a lè lò nínú ayé wa ní òní.

Ní òní, bí a ti wi, à ndarapọ̀ mọ́ àwọn onígbàgbọ́ káàkiri àgbáyé láti buọlá fún Jésù Krístì ní Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ yí. Ní bíi ẹgbẹ̀rún ọdún méjì sẹ́hìn, Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ fi àmì sí ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀sẹ̀ ìkẹhìn ti iṣẹ́ ìránṣẹ́ ayé ikú Jésù Krístì. Ó jẹ́ pàtàkì jùlọ nínú àkọọ́lẹ̀-ìtàn ènìyàn.

Ohun tí ó bẹ̀rẹ̀ kíkéde Jésù Krístì tí a ṣe ìlérí ní ìsẹ́gun wíwọ inú Jerusalem Rẹ̀ ní sísúnmọ́ ìkànmọ́ àgbélèbú àti Àjínde Rẹ̀.1 Nípa àwòṣe tọ̀run, Ètùtù Ìrúbọ Rẹ̀ parí iṣẹ́ ìránṣẹ́ ayé ikú Rẹ̀, ó sì mu ṣeéṣe fún wa láti gbé pẹ̀lú Baba wa Ọ̀run fún àìlópin.

Àwọn ìwé mímọ́ sọ fún wa pé ọ̀sẹ̀ náà bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àwọn èrò tí wọ́n dúró ní ẹnu ọ̀nà ìlú láti rí “Jésù wòlíì ti Nazareth Galilee.”2 Wọ́n “mú ẹ̀ka igi màrìwò ọ̀pẹ, wọ́n sì lọ síwájú láti pàdé rẹ̀, wọ́n sì nké: Hòsánnà: Alábùkún ni Ọbá Ísráẹ́lì tí ó nbọ̀ ní orúkọ Olúwa.”3

Àkọsílẹ̀ ti Bíbélì náà tí ó ti pẹ́ gan rán mi létí wíwà ní yíyàn síṣẹ́ Ìjọ ní Takoradi, Ghana. Pẹ̀lú ìyanu, mo wà níbẹ̀ ní Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ.

Àwòrán
Àwọn ìjọ ní Takoradi, Ghana

Mo níláti pín Èèkàn Takoradi Ghana láti dá Èèkàn Mpintsin Ghana sílẹ̀. Ní òní, àwọn ọmọ Ìjọ ẹgbẹ̀rún ọgọ́ọ̀rún kan ni ó wà ní Ghana.4 (A kí ẹni-ọ̀wọ́ Ọlọ́lá jùlọ Ọba Nii Tackie Teiko Tsuru II ti Accra, Ghana, ẹnití ó wà pẹ̀lú wa lóni.) Ní pípàdé àwọn Ènìyàn Mímọ́ wọ̀nyí, mo ní ìmọ̀lára ìfẹ́ ìjìnlẹ̀ àti ìfọkànsìn wọn sí Olúwa. Mo fi ìfẹ́ títóbi mi hàn fún wọn àti pé Ààrẹ Ìjọ fẹ́ràn wọn. Mo tọ́ka sí àwọn ọ̀rọ̀ Olùgbàlà tí a kọsílẹ̀ láti ọwọ́ Jòhánù: “Kí ẹ fẹ́ràn ara yín, bi èmi ti fẹ́ràn yín.”5 Wọ́n sọ ọ́ di “Mo fẹ́ràn ìpàdé àpapọ̀.”6

Àwòrán
Alàgbà Rasband nbọni lọ́wọ́ ní Takoradi, Ghana

Bí mo ti nwòkè àti ilẹ̀ àwọn ìlà ti àwọn arákùnrin àti aràbìnrin àti ẹbí wọn nínú ilé ìjọsìn, mo lè rí dídán ẹ̀rí àti ìgbàgbọ́ nínú Jésù Krístì ní ojú wọn. Mo ní ìmọ̀lára ìfẹ́ wọn láti jẹ́ ara ìlọsíwájú Ìjọ Rẹ. Àti pé nígbàtí àwọn akọrin nkọrin wọ́n kọrin bí àwọn ángẹ́lì.

Àwòrán
Àwọn akọrin ní Takoradi, Ghana.
Àwòrán
Alàgbà Rasband pẹ̀lú àwọn ọmọ ìjọ ní Ghana

Bíi Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ àtijọ́, ìwọ̀nyí ni àwọn ọmọẹ̀hìn Jésù Krístì tí wọ́n kórajọ láti gbé oríyìn fún Un bí àwọn wọnnì ní ẹnu ọ̀nà Jerusalem ti ṣe tí wọ́n wà, pẹ̀lú màrìwò ọ̀pẹ ní ọwọ́ wọn, kígbe, “Hòsánnà … : Alábùkún ni ẹni tí ó nbọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.”7

Àwòrán
Jíju màrìwò sóke ní Ghana

Àní àwọn òṣìṣẹ́ nínú ìjọ ni wọ́n nbu ọlá fún Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ. Bí mo ti nsọ̀rọ̀ láti orí pẹpẹ, mo ní àkíyèsí láti ojú fèrèsé tí wọ́n nfi tayọtayọ rìn lọ sí pópónà tí wọn nju màrìwò ọ̀pẹ ní ọwọ́ wọn sókè, ní púpọ̀ bí àwọn tí ó wà nínú fọ́tò yí Ó jẹ́ ìwò kan tí èmi kò ní gbàgbé láéláé—gbogbo wa ní ọjọ́ náà wà níjíjọ́sìn Ọba àwọn Ọba.

Ààrẹ Russell M. Nelson ti kìlọ̀ fún wa láti mú Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ jẹ́ “mímọ́ nítòótọ́ nípa rírántí, kìí ṣe àwọn màrìwò tí à njùsókè láti buọlá fún wíwọlé Jésù sí Jerusalem nìkan, ṣùgbọ́n nípa rírántí àwọn àtẹ́lẹwọ́ ti ọwọ́ Rẹ̀.” Nígbànáà Ààrẹ Nelson tọ́ka sí Isaiah, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ nípa Olùgbàlà tí ó ṣe ìlérí pé, “Èmi kò ní gbàgbé yín láéláé,”pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí: “Kíyèsi, mo ti gbé yín lé orí àtẹ́lẹwọ́ ọwọ́ mi.”8

Olúwa mọ̀ ní àkọ́kọ́ pe ayé ikú le. Àwọn àpá Rẹ̀ rán wa léti pé Òun ti “sọ̀kalẹ̀ kọjá … ohun gbogbo”9 kí Òun lè tù wá nínú nígbàtí a bá njìyà kí ó sì jẹ́ àpẹrẹ wa láti “dúró ní ọ̀nà rẹ,”10 Ọ̀nà Rẹ̀, kí “Ọlọ́run lè wà pẹ̀lú [wa] títíláé àti láéláé.”11

Ọjọ́ Ìsìnmi Ọ̀pẹ kìí ṣe ìṣẹ̀lẹ̀ nìkan, ojú ewé míràn nínú àkọọ́lẹ̀-ìtàn pẹ̀lú ọjọ́ kan, àkokò àti ibìkan ni. Jésù Krístì fi ẹ̀yẹ wọnú Jerusalem àti pé àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ti ọ̀sẹ̀ náà tí ó tẹ̀lé e jẹ́ àpẹẹrẹ ẹ̀kọ́ tí a lè lò nínú ayé wa lónìí.

Ẹ jẹ́ kí a wo àwọn ẹ̀kọ́ ayérayé kan tí ó wémọ́ ìparí iṣẹ́ ìránṣẹ́ ní Jerúsálẹ́mù.

Àkọ́kọ́, àsọtẹ́lẹ̀. Fún àpẹrẹ, wòlíì Zechariah sọtẹ́lẹ̀ nípa fífi ẹ̀yẹ̀ wọ̀nú Jésúsálẹ́mù Jésù Krístì, àní jíjúwe pé Òun yíò gun orí dọ́nkì.12 Jésù sọ̀rọ̀ Àjínde Rẹ̀ síwájú bí Ó ti múrasílẹ̀ láti wọnú ìlú, ó wípé:

“Kíyèsi, à nlọ sí Jérúsálẹ́mù; a ó sẹ́ Ọmọ ènìyàn sí àwọn àlùfáà àti àwọn agbowóde, wọn ó sì da lẹ́bi ikú.

“Wọn ó sì fi lé àwọn Gentile lọ́wọ́ láti kẹ́gàn, àti láti kàn án mọ́ àgbélèbú: ós ì jí dìde ní ọjọ́ kẹ́ta, .”13

Ìkejì, olùbárin Ẹ̀mí Mímọ́. Joseph Smith kọ́ni pé, “Kò sí ènìyàn kankan tí ó lè mọ̀ pé Jésù ni Olúwa, bíkòṣe nípa Ẹ̀mí Mímọ́.”14 Olùgbàlà ṣe ìlérí fún àwọn ọmọẹ̀hìn Rẹ̀ pé15 ní bi Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn16 ní yàrá òke,17 “Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láé ní ìtùnú.”18 Wọn kò ní dánìkan wà láti gbé àwọn òtítọ́ ìhìnrere síwájú ṣùgbọ́n wọn ìbá ti ní àṣepé ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ láti tọ́ wọn sọ́nà. “Àláfíà ni mo fi sílẹ̀ fún yín, àláfíà mi ni mo fún yín,” Ó ṣe ìlérí; “kìí ṣe bí ayé ti í funni, ni èmi fi fún yín.”19 Pẹ̀lú ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ a ní irú ìdánilójú kannáà—pé a “lè ní Ẹ̀mí rẹ̀ pẹ̀lú [wa] nígbàgbogbo”20 àti pé “nípa agbára Ẹ̀mí Mímọ́ [a] lè mọ òtítọ́ ohun gbogbo.”21

Ìkẹ́ta, jíjẹ́ ọmọlẹ́hìn. Jíjẹ́ ọmọlẹ́hìn tòótọ́ ni ìfaramọ́ àìkùnà, ìgbọràn sí àwọn òfin ayérayé, àti ìfẹ́ Ọlọ̀run, àkọ́kọ́ àti ìṣíwájú jùlọ. Láì ṣiyèméjì. Ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn tí wọ́n gbé oríyìn pẹ̀lú màrìwò ọ̀pẹ yìn In bí Mesiah. Ìyẹn ni ẹni tí Òun jẹ́ gàn. Wọ̀n sún mọ́ Ọ, àwọn iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀, àti àwọn ìkọ́ni Rẹ̀. Ṣùgbọ́n ìpọ́nni fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ kò pẹ́. Àwọn kan tí wọ́n ti kígbe ṣíwájú, “Hosanna”22 láìpẹ́ yípadà wọ́n sì ké pé, “Kàn án mọ́ àgbélèbú.”23

Ìkẹ́rin, Ètùtù Jésù Krístì.24 Ní àwọn ọjọ́ ìkẹhìn Rẹ̀, títẹ̀lé Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ, Ó gbé Ètùtù olókìkì Rẹ̀ jáde, látinú ìrora Gethsemane sí ẹ̀sín àdánwò Rẹ̀, ìpalára Rẹ̀ lórí àgbélèbú, àti ìsìnkú Rẹ̀ ní ìsà-òkú yíyá. Ṣùgbọ́n kò dúró níbẹ̀. Pẹ̀lú ìpè ọlọ́lá Rẹ̀ bí Olùràpadà gbogbo àwọn ọmọ Baba Ọ̀run, ọjọ́ mẹ́ta lẹ́hìnnáà Ó jáde wá látinú isà-òkú náà, ó jínde,25 bí Ó ti sọtẹ́lẹ̀.

Ṣé à nfi ìmoore hàn lóòrèkóòrè fún Ètùtù àìláfiwé ti Jésù Krístì? Njẹ́ a ní ìmọ̀lára ti agbára ìyàsímímọ́ rẹ, báyìí nísisìyí? Iyẹn ni ìdí tí Jésù Krístì, Olùpilẹ̀ṣẹ̀ àti Aláṣetán Ìgbàlà wa, fi lọ sí Jérúsálẹ́mù, láti gba gbogbo wa la. Njẹ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nínú Álmà gún ni: “Bí ẹ̀yin bá ti rí ìyípadà ọkàn, tí ẹ̀yin bá sì fẹ́ láti kọ orin ìfẹ́ ti ìràpadà, mo bẽrè, ṣé ẹ̀yin lè ṣe bẹ̃ nísisìyí?”26 Mo lè sọ nítòótọ́, akọrin ní Takoradi ní Ọjọ́ ìsinmi Ọ̀pẹ ti kọ ”orin ìfẹ́ ìràpadà.”

Ní ọ̀sẹ tí ó kẹ́hìn ti iṣẹ́ ìránṣẹ́ ayé ikú Rẹ̀, Jésù Krístì fúnni ní òwe àwọn wúndíá mẹwa.27 Ó kọ́ni nípa ìpadàbọ̀ Rẹ̀ sí àwọn wọnnì tí wọ́n múrasílẹ láti gbà Á, kìí ṣe pẹ̀lú màrìwò ọ̀pẹ ní ọwọ́ wọn ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ìhìnrere nínú wọn. Ó lo àwòrán ti fìtílà tí a tàn tí ó sì njó, pẹ̀lú òróró ṣíṣẹ́kù láti mu jó, bí ìjúwe ti ìfẹ́ láti gbé ní ọ̀nà Rẹ̀, gba òtítọ́ Rẹ̀ mọ́ra, àti pín ìmọ́lẹ̀ Rẹ̀.

Ẹ mọ ìtàn náà. Àwọn wúndíà mẹwa ṣojú àwọn ọmọ Ìjọ, àti ọkọ ìyàwó ṣojú Jésù Krístì.

Àwọn wúndíà mẹwa gbé fìtílà wọn wọ́n sì “lọ síwájú láti pàdé ọkọ-ìyàwó.”28 Marun jẹ́ ọlọgbọ́n, wọ́n múrasílẹ̀ pẹ̀lú òróró nínú fìtílà àti díẹ̀ láti tọrẹ, àti pé marun jẹ́ aláìgbọ́n, fìtílà kú láìsí òróró ní ìpamọ́. Nígbatí ìpè wá, “Kíyèsi, ọkọ-ìyàwó dé; ẹ jáde kí ẹ lọ í pàdé rẹ̀,”29 àwọn marun tí wọ́n “gbọ́n tí wọ́n sì [ti] gba òtítọ́, tí wọ́n sì [ti] gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí atọ́nà wọn”30 ti ṣetán fún “ọba wọn àti aṣòfin wọn,”31 pé “ògo rẹ̀ [yíò] wà lórí wọn.”32 Àwọn marun míràn ngbìyànjú tipátipá láti rí òróró. Ṣùgbọ́n ó ti pẹ́ jù. Ìrìn náà lọ síwáju láìsí i wọn. Nígbàtí wọ́n kànkù tí wọ́n sì bẹ̀bẹ̀ fún wíwọlé, Olúwa fèsì pé “Èmi kò mọ̀ yín.”33

Báwo ni a ó ṣe ní ìmọ̀lára bí Òun bá wí fún wa pé, “Èmi kò mọ̀ yín!”

Àwa, bíi ti wúndíà mẹwa, ní fìtílà; ṣùgbọ́n njẹ́ a ní òróró? Mo bẹ̀rù pé àwọn kan tí wọ́n kàn ngbáyé ní etí orí òróró tíntín, wọn kò ráyè nítorí àwọn ìgbádùn ti ayé kò jẹ́ kí wọ́n múra dáradára Òróró nwá látinú gbígbàgbọ́ àti ṣíṣe ìṣe lórí àsọtẹ́lẹ̀ àti ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì alààyè, Ààrẹ Nelson ní pàtàkì, àwọn Olùdámọ̀ràn rẹ̀, àti àwọn Àpóstélì Méjìlá. Òróró nkún inú ẹ̀mí wa nígbàtí a bá gbọ́ tí a sì ní ìmọ̀lára Ẹ̀mí Mímọ́ àti ìṣe lórí ìtọ́sọ́nà tọ̀run. Òróró ndà sínú ọkàn wa nígbàtí àwọn àṣàyàn wa ba fihàn pé a ní ìfẹ́ Olúwa kí a sì fẹ́ràn ohun tí Ó fẹ́ràn. Òróró nwá látinú ìrònúpìwàdà àti wíwá ìwòsàn ti Ètùtù Jésù Krístì.

Bí ẹ bá nwá láti kún inú ohun tí àwọn kan pè ní “ìtò garawa kan,” èyí ni kí: Ẹ kún garawa yín pẹ̀lú òróró ní àwòrán ti omi ìyè Jésù Krístì,34 èyí ni aṣojú ìgbé ayé àti ìkọ́ni Rẹ̀. Ní ìlòdì, fífi àmì sí ibi jíjìnréré tàbí ìṣẹ̀lẹ̀ híhàn tí kò ní fi ìmọ̀lára ẹ̀mí yín sílẹ̀ lódidi tàbí ìtẹlọ́run láé; gbígbé ẹ̀kọ́ tí a kọ́ni láti ẹnu Jésù Krístì yíò ṣe. Mo dárúkọ wọn ṣíwájú: ẹ rọ̀mọ́ àsọtẹ́lẹ̀ àti àwọn ìkọ́ni ti wòlíì, ẹ ṣe ìṣe lórí àwọn ìṣíletí ti Ẹ̀mí Mímọ́, di ọmọẹ̀hìn tòótọ́, àti wíwá agbára ìwòsàn Ètùtù Olúwa wa. Ìtò garawa náà yíò gbé yín dé ibìkan tí ẹ fẹ́ láti lọ—padà sí ọ̀dọ̀ Baba ní Ọ̀run.

Ọjọ́ Ìsinmi Ọ̀pẹ́ náà ní Takoradi jẹ́ ìrírí pàtàkì gan fún mi nítorí tí mo pín in pẹ̀lú àwọn olotitọ ìjọ arákùnrin àti arábìnrin. Nítorínáà ó ti wà ní kọ́ntínẹ̀ntì àti àwọn erékùṣù kárí ayé. Ọkàn àti ẹ̀mí mi, bíi tiyín, nlọ́ra láti ké, “Hòsánnà sí Ọlọ́run Gíga Jùlọ.”35

Bíótilẹ̀jẹ́pé a kò dúró ní ẹnu ọ̀nà Jerusalem ní òní pẹ̀lú àwọn màrìwò ní ọwọ́ wa, àkokò náà yíò wá nígbàtí, bí a ti sọtẹ́lẹ̀ nínú Ìfihàn, “ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn púpọ̀, èyí tí ẹ̀nìkẹ́ni kò lè ka oye, gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè, àti ìdílé, àti ènìyàn, àti èdè, [yíò dìde] níwájú ìtẹ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-àgùtàn, tí a wọ ní aṣọ fúnfún, àti màrìwò ní ọwọ́ wọn.”36

Mo fi ìbùkún mi bí Àpóstélì Jésù Krístì sílẹ̀ pẹ̀lú yín pé ẹ ó fi aápọn tiraka láti gbé ìgbé òdodo àti láti wà ní àárín àwọn wọnnì tí wọ́n wà, pẹ̀lú màrìwò ní ọwọ́ wọn, yío kéde Ọmọ Ọlọ́run, Olùràpadà nlá gbogbo wa. Ní orúkọ Jésù Krístì, àmín.

Àwọn Àkọsílẹ̀ ránpẹ́

  1. Gbogbo àwọn ìhìnrere mẹ́rin—Matteu 21–28; Mark 11–16; Luke 19-24; àti John 12–21—ṣe àpèjúwe àwọn ọjọ́ ìkẹhìn iṣẹ́ ìránṣẹ́ Jésù Krístì nínú ayé ikú, èyí ni àwòṣe tọ̀run láti mú àwọn ìbùkún ìgbàlà àti ìgbéga wà fún gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run. Ní ìgbà míràn àwọn olùpìlẹ̀ṣẹ yàtọ̀ nínú ohun tí wọ́n mú

  2. Wo Máttéù 22:37–39

  3. John 12:46.

  4. Ní Ọmọ ìjọ kọ̀ọ̀kan áti àwọn Ìṣirò Àkọsílẹ̀, àwọn ọmọ ìjọ 102,592 ni ó wà ní Ghana.

  5. John 15:12.

  6. Ní gbogbo ìgbà tí mo bá sọ̀rọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ ìjọ, wọn yíò wí fún mi pé, “Alàgbà Rasband, Àpóstélì wa ọ̀wọ́, mo ní ìfẹ́ yín.” Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ni ó

  7. Matteu 21:9

  8. Wo Russell M. Nelson, “Àláfíà àti Ìrètí Ọdún Àjínde” (video), Apr. 2021, ChurchofJesusChrist.org/media; Isaiah 49:16.

  9. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 122:8. Ní Oṣù Kẹjìlá 1838 Wòlíì Joseph àti díẹ̀ lára àwọn olórí Ìjọ míràn ni a tìmọ́lé láìtọ́ ní ẹ̀wọ̀n Liberty. Àwọn ipò náà foniláyà. Lẹ́hìn àwọn oṣù ní ipò abòṣì, ó kọ̀wé sí àwọn ọmọ ìjọ ní Oṣù Kẹta ti 1839, pẹ̀lú àdúrà níbití ó ti bẹ Olúwa láti ní àánú lórí ipò rẹ̀ àti “àwọn olùjìyà Ènìyàn Mímọ́.” Bákannáà ó pín ìfèsì Olúwa sí àwọn àdúrà wọnnì bí a ti kọ́sílẹ̀ nínú Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 121–23.

  10. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 122:9. Ìgbàni-nìyànjú Olúwa sí Josèph Smoth ní Ẹ̀wọ̀n Líberty mú ìtùnú wá fún un àti ìmọ̀ ti-ẹ̀mí pé ìpọ́njú àti àdánwò lè fún wa lókun, kọ́ wa ní sùúrù, àti ìkọ́raẹni-lọ́gbọ́n. Olúwa pè é kí ó “di ọ̀nà rẹ mú,” èyí tí ó jẹ́ ọ̀nà Olúwa, ní fífarada ìwà àìtọ́ bí i ti “Ọmọ [Ọlọ́run, ẹnití] ó sọ̀kalẹ̀ lábẹ́ gbogbo wọn. Ṣé ìwọ tóbi jùú lọ? Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 122:8).

  11. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 122:9. Ẹ̀bẹ̀ náà pé Ọlọ́run “yíò wà pẹ̀lú rẹ” ni ìlérí tí ó dájú fún àwọn ẹnití wọ́n di ìgbàgbọ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé wọn mú daindain nínú Olúwa.

  12. Wo Zechariah 9:9.

  13. Matteu 20:18–19. James E. Talmage kọ̀wé nínú Jésù Krístì Náà: “Ó jẹ́ … òtítọ́ dìdùnlẹ pé àwọn Méjìlá kùnà láti ní òye ìtumọ̀ Rẹ̀. … Sí wọn àwọn ìfòyà àìnì-ìbámu kan wà, àwọn ìdíwọ́ líle yíyẹsẹ̀ tàbí àìnìtumọ̀ nínú ọ̀rọ̀ sísọ àyànfẹ́ Olùkọ́ni wọn. Wọ́n mọ̀ Ọ pé Ó jẹ́ Krístì, Ọmọ Ọlọ́run alààyè; àti pé báwo ni a ó ṣe mú irú Ọ̀kan bẹ́ẹ̀ wá sínú ìgbèkùn kí a sì pa á?” ([1916], 502–3).

  14. Joseph Smith ṣe ìkede yí sí àwọn Obìnrin Ẹgbẹ́ Ìrànlọ́wọ́ Nauvoo, April 28, 1842, bí a ti ṣe àyọsọ nínú “Àkọọ́lẹ̀-ìtàn ti Joseph Smith,” Deseret News, Sept. 5, 1855. Títọ́kasí orí Kejìlá ti 1 Corinthians, ó yanjú e ẹsẹ kẹ́ta, “Kò sí ènìyàn kankan tí ó lè wípé Jésù ni Olúwa, bíkòṣe nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́,” ó tunsọ pé, “Kò sí ènìyàn kankan tí ó lè mọ̀ pé JÉsù ni Olúwa bíkòṣe nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́.” (Wo Àádọ́ta Ọdún Àkọ́kọ́ ti Ẹgbẹ́ Ìrànlọ́wọ́: Àwọn Ìwé Pàtàkì nínú Àkọ́ọlẹ̀-ìtàn Àwọn Obìnrin Ènìyàn Mímọ́ Ajọ́-ìkẹhìn [2016], 2.2, churchhistorianspress.org.)

  15. Jésù pín Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn pẹ̀lú àwọn ọmọẹ̀hìn Rẹ̀ (wo Mark 14:12–18). Àwọn méjìlá pẹ̀lú Peter, Andrew, James, John, Matthew, Philip, Thomas, Bartholomew, James (ọmọ Alphaeus), Judas Iscariot, Judas (arákùnrin Jákọ́bù), àti Simon (wo Luke 6:13–16).

  16. Jésù fi oúnjẹ́ Olúwa lọ́lẹ̀ pẹ̀lú àwn ọmọẹ̀hìn Rẹ̀ níbi Oún Alẹ́ Ìkẹhìn (wo Matthew 26:26–29; Mark 14:22–25; Luke 22:19–20).

  17. Kókó ọjọ́/alẹ́ nínú èyí tí Jésù gbé Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn kalẹ̀ nínú “yàrá òkè” ni wọ́n jiyàn rẹ̀ lódodo nítorí ó dàbí àìbáramu ní àárín Matthew, Mark, àti Luke àti John. Matthew, Mark, àti Luke dá àbá pé Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn ṣẹlẹ̀ ní “ọjọ́ ìkínní àkàra àìléru,” tàbí oúnjẹ Ìrékọjá ( wo Matthew 26:17; Mark 14:12; Luke 22:1, 7). John, bákannáà, dá àbá pé a mú Jésù ṣíwájú oúnjẹ Ìrékọjá (wo John 18:28), ó túmọ̀ sí pé Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn ìbá ti ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ kan ṣíwájú ju oúnjẹ Ìrékọjá. Ìwé èlò kíkà Ìjọ àti dídánilẹ́ẹ̀kọ́ àwọn Ènìyàn Ọjọ́-ìkẹhìn dàbí ó faramọ pé Jésù ṣe Óunjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn pẹ̀lú àwọn ọmọẹ̀hìn Rẹ̀ ní yàrá òkè ní ìrọ̀lẹ́ ṣíwájú kí a tó kàn An mọ́ àgbélèbú. Àwọn onígbàgbọ́ nṣe ayẹyẹ Ọ̀sẹ̀ Mímọ́ ní ìdámọ̀ Ọjọ́bọ̀ bí ọjọ́ Oúnjẹ Alẹ́ Ìkẹhìn, Ẹ̀ti bí ọjọ́ Ìkànmọ́-àgbélèbú, àti Ọjọ́ Ìsinmi bí Ọjọ́ Àjìnde—gẹ́gẹ́bí kàlẹ́ndà Gregorian.

  18. John 14:18.

  19. Johanu 14:27.

  20. Ẹ̀kọ́ àti Àwọn Májẹ̀mú 20:77.

  21. Mórónì 10:5.

  22. Ìtumọ̀ Bíbélì ṣe àlàyé pé, hosanna túmọ̀sí “pamọ́ nísisìyí.” Ọ̀rọ̀ náà ni a mú látinú Psalm 118:25. “Sísọ Orin Dáfídì yí sopọ̀ mọ́ Ayẹyẹ Àgọ́ pẹ̀lú jíju ẹ̀yà màriwò; tí ó fa lílo ọ̀rọ̀ nípa ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn níbi fífi ìṣẹẹ́gun wọ Jérúsálẹ́mù Olúwa” (Bible Dictionary, “Hosanna”). Wo Matthew 21:9, 15; Mark 11:9–10; John 12:13.

  23. Mark 15:14; Luke 23:21.

  24. Gbùngbun ètò ìgbàlà Baba wa Ọ̀run jẹ́ Ètùtù àìlópin tí yíò mú àìkú dájú fún gbogbo àwọn ọmọ Rẹ̀ àti ìgbéga fún àwọn yíyẹ láti gba ìbùkún náà. Nígbàtí Bàbá Rẹ̀ béèrè, “Tàni Èmi ó rán?” Jésù Krístì wá síwájú, “Èmi wà nihin; rán mi” (Abraham 3:27). Àarẹ Russell M. Nelson ti kọ̀ni: “iṣẹ́ ìhìnrere ti [Jesu Krístì] ni Ètùtù náà. Iṣẹ́ ìhìnrere náà jẹ́ àìláfiwé Tirẹ̀. A bi láti ara ìyá ayé ikú àti Baba àìkú, Òun ni ẹnìkanṣoṣo tí ó fi ìdùnnú gbé ayé Rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbé e sókè lẹ́ẹ̀kansi (wo John 10:14–18). Àbájáde ológo ti Ètùtù Rẹ̀ jẹ́ àìlópin àti ayérayé. Ó mú oró ikú jáde ó sì mú ìbànújẹ́ ránpẹ́ ti isà-òkú kúrò (wo 1 Corinthians 15:54–55). Ojúṣe Rẹ̀ fún Ètùtù ni a mọ̀ àní ṣíwàjú Ìṣẹ̀dá àti Ìṣubú. Kìí ṣe pé ó jẹ́ láti pèsè fún àjínde àti àìkú ti gbogbo enìyàn ayé nìkan, ó jẹ́ láti mú wa ní ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa—lórí àwọn ipò tí a gbékalẹ̀ nípasẹ̀ Rẹ̀. Bayi Ètùtù Rẹ̀ Ṣí ọ̀nà nípa èyí tí a fi lè ní ìdàpọ̀ pẹ̀lú Rẹ̀ àti pẹ̀lú àwọn ẹbí wa ní ayérayé” (“Iṣẹ́ Ìhìnrere àti Iṣẹ́ Ìránṣẹ́ ti Jésù Krístì,” Làìhónà, Apr. 2013, 20).

  25. Àjínde wà pẹ̀lú títúnsopọ̀ ara àti ẹ̀mí ní ipò àìkú, ara àti ẹ̀mí jẹ́ àìlèyàsọ́tọ̀ tí kò sì somọ́ àwọn wàhálà ayé ikú tàbí ikú (wo Alma 11:45; 40:23).

  26. Alma 5:26; bákannáà wo Alma 5:14.

  27. Òwe àwọn wúndíá mẹwa tí a rí ní Matthew 25:1–12; Doctrine and Covenants 45:56–59. Àwọn ori àyíká ti Matthew 25dá àbá pé Jesu kọ́ni ní àwe yí ní ìgbà ọ̀sẹ̀ tí kẹ́hìn, lẹ́hìn wíwọ Jerusalem Matteu 21 àti ṣíwájú Oúnjẹ́ Alẹ́ Ìkẹhìn àti mímú Rẹ̀ ní Matthew 26. Ní àfikún sí òwe àwọn wúndíá mẹwa tí a fúnni ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá, Jesu fúnni ní òwe igi ọ̀pọ̀tọ́ (wo Matthew 21:17–21; 24:32–33) òwe ọmọ méjì (wo Matthew 21:28–32), òwe ọba ọgbà àjàra búburú (wo Matthew 21:33–46).

  28. Máttéù 25:1.

  29. Máttéù 25:6.

  30. Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 45:57.

  31. Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 45:59.

  32. Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 45:59.

  33. Máttéù 25:12. Nínú Ìwàásù orí Òkè, Olúwa tọ́ka sí àwọn tí wọ́n ró pé wọ́n ti ṣe “ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ ìyanu,” ó wípé, bí a ti daba nínú àkọsílẹ̀ àwọn wúndíà marun tí kò gbọ́n, “Èmi kò mọ̀ ọ́” (wo Matthew 7:22–23).

  34. Gẹ́gẹ́bí omi ti ṣe kókó sí ara ikú, Jésù Krístì àti àwọn ìkọ́ni Rẹ̀ (omi ìyè) ṣe kókó sí ìyè ayérayé (wo ìtọ́sọ́nà sí àwọn ìwé mímọ́, “Omi Ìyè,” scriptures.ChurchofJesusChrist.org; bákannáà wo Isaiah 12:3; Jeremiah 2:13; John 4:6–15; 7:37; 1 Nefi 11:25; Ẹ̀kọ́ àti àwọn Májẹ̀mú 10:66; 63:23).

  35. 3 Nèfì 4:32.

  36. Ìfihàn 7:9.

Tẹ̀